Ìwé Wòlíì Mika
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
2 Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,
fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,
kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,
[a]Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu
3 Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;
yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
4 Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,
àwọn àfonífojì yóò sì pínyà,
bí idà níwájú iná,
bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
5 Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,
àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.
Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?
Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?
Kí ni àwọn ibi gíga Juda?
Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
6 “Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,
bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.
Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.
Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
7 Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́
gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun,
Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.
Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,
gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
Ẹkún òun ọfọ̀
8 Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,
èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:
èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò.
Èmi yóò ké bí akátá,
èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
9 Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;
ó sì ti wá sí Juda.
Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,
àní sí Jerusalẹmu.
10 Ẹ má ṣe sọ ní Gati
ẹ má ṣe sọkún rárá.
Ní ilẹ̀ Beti-Ofra
mo yí ara mi nínú eruku.
11 Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,
ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.
Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani
kì yóò sì jáde wá.
Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;
a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
12 Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,
ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
13 Ìwọ olùgbé Lakiṣi,
dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.
Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀
sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,
nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
14 Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀
fún Moreṣeti Gati.
Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
15 Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.
Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli
yóò sì wá sí Adullamu.
16 Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀
nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,
sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,